2 Kíróníkà 29:12-18 BMY

12 Nígbà náà àwọn ọmọ Léfì wọ̀nyí múra láti ṣe iṣẹ́:nínú àwọn ọmọ Kóhátì,Máhátì ọmọ Ámásà: àti jóẹ́lì ọmọ Ásáríyà;nínú àwọn ọmọ Mérárì,Kíṣì ọmọ Ábídì àti Ásáríyà ọmọ Jéháiéíèlì;nínú àwọn ọmọ Gésónì,Jóà, ọmọ símà àti Édẹ́nì ọmọ Jóà;

13 nínú àwọn ọmọ Élisáfánì,Ṣímírì àti Jégíèlì;nínú àwọn ọmọ Ásáfù,Sékáríà àti Mátaníyà;

14 nínú àwọn ọmọ Hémánì,Jéhíélì àti Ṣíméhì;nínú àwọn ọmọ Jédútùnì,Ṣémáíà àti Húsíélì.

15 Nigbà tí wọ́n sì ti kó ara wọn jọ pọ̀ pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn, wọ́n sì ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì lọ láti gbá ile Olúwa mọ́, gẹ́gẹ́ bí ọba ti paáláṣẹ, ẹ tẹ̀lé ọ̀rọ̀ Olúwa.

16 Àwọn àlùfaà sì wọ inú ilé Olúwa lọ́hùn ún lọ láti gbá a mọ́. Wọ́n sì gbé e jáde sí inú àgbàlá ilé Olúwa gbogbo ohun àìmọ́ tí wọ́n rí nínú ilé Olúwa. Àwọn ọmọ Léfì sì mú u wọ́n sì gbé e jáde sí gbangba odò Kédírónì.

17 Wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ ìyà sí mímọ́ ní ọjọ́ kìn-ín-ní osù kìn-ín-ní, àti ní ọjọ́ kẹjọ oṣù náà wọ́n sì dé ìloro Olúwa. Fún ọjọ́ mẹ́jọ mìíràn síi, wọ́n sì ya ilé Olúwa sí mímọ́ fún rarẹ̀. Wọ́n sì parí ní ọjọ́ kẹ́rìndínlógún oṣù kìn-ín-ní.

18 Nígbà náà wọn sì lọ sí ọ̀dọ̀ ọba Héṣékíà láti lọ jábọ̀ fún un: “Àwa ti gbá ilé Olúwa mọ́, pẹpẹ ẹbọ sísun pẹ̀lú gbogbo ohun ẹbọ rẹ̀, àti tábìlì àkàrà ìfihàn, pẹ̀lú gbogbo ohun èlò.