28 Ó kọ́ àwọn ilé pẹ̀lú láti tọ́jú àwọn ọkà àwọn tí wọ́n ka, ọtí titun àti òróró; ó sì ṣe àwọn àtíbàbà fún oríṣìí àwọn ẹran ọ̀sìn àti àwọn àsémọ́ fun àwọn ọ̀wọ̀ ẹran.
29 Ó kọ́ àwọn ìletò, ó sì gba ọ̀pọ̀ iye àwọn ọ̀wọ́ ẹran àti agbo ẹran, nítorí tí Olúwa ti fún un ní ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ńlá.
30 Heṣekíà ni ó dí ojú ìṣúra apá òkè ti orísun Gíhónì. Ó sì gbe gba ìsàlẹ̀ sí ìhà ìwọ oòrùn ìlú ńlá ti Dáfídì. Ó ṣe àṣeyọrí sí rere nínu gbogbo ohun tí ó dáwọ́lé.
31 Ṣùgbọ́n nígbà tí ara àwọn oníṣẹ́ ọba wá láti Bábílónì láti bi í lérè nípa àmìn ìyanu tí ó sẹlẹ̀ nì, Ọlọ́run fi sílẹ̀ láti dán an wò àti láti mọ gbogbo nǹkan tí ó wà lọ́kàn rẹ̀.
32 Gbogbo iṣẹ́ yòókù ti ìjọba Heṣekíà àti àwọn ìṣe rẹ̀, ìfarajì rẹ̀ ni a kọ sínú ìwé ìran wòlíì Àìṣáyà ọmọ Ámósì nínú ìwé àwọn ọba Júdà àti Ìsírẹ́lì
33 Heṣekáyà sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. A sì sin-ín sórí òkè níbi tí àwọn ibojì àwọn àtẹ̀lé Dáfídì wà. Gbogbo Júdà àti àwọn ènìyàn Jérúsálẹ́mù ni ó bu ọlá fún un nígbà tí ó kú. Mánásè ọmọ rẹ̀ sì rọ́pò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.