2 Ọba 13:13-19 BMY

13 Jéhóásì sinmi pẹ̀lú àwọn baba a rẹ̀. Jéróbóámù sì rọ́pò rẹ̀ lórí ìtẹ́. A sin Jéhóásì sí Samáríà pẹ̀lú àwọn ọba Ísírẹ́lì.

14 Nísinsìn yìí, Èlíṣà ń jìyà lọ́wọ́ àìsàn, lọ́wọ́ èyí tí ó sì kú. Jéhóásì ọba Ísírẹ́lì lọ láti lọ wò ó, ó sì ṣunkún lórí rẹ̀. “Baba mi!, Baba mi!” Ó ṣunkún. “Àwọn kẹ̀kẹ́ àti àwọn ọkùnrin ẹlẹ́ṣin Ísírẹ́lì.!”

15 Èlíṣà wí pé, “Mú ọrun kan àti àwọn ọfà,” ó sì ṣe bẹ́ẹ̀.

16 “Mú ọrun ní ọwọ́ rẹ.” Ó wí fún ọba Ísírẹ́lì. Nígbà tí ó ti mú u, Èlíṣà mú ọwọ́ rẹ̀ lé ọwọ́ ọba.

17 “Ṣí fèrèsé apá ìlà oòrùn,” ó wí, pẹ̀lú ó sì ṣéé: “Ta á!” Èlíṣà wí, ó sì ta á. “Ọfà ìṣẹ́gun Olúwa; ọfà ìṣẹ́gun lórí Ṣíríà!” Èlíṣà kéde. “Ìwọ yóò pa àwọn ará Ṣíríà run pátapáta ní Áfékì.”

18 Nígbà náà ó wí pé, “Mú àwọn ọfà náà,” ọba sì mú wọn. Èlíṣà wí fún un pé, “Lu ilẹ̀.” Ó lù ú lẹ́ẹ̀mẹ́ta, ó sì dáwọ́ dúró.

19 Ènìyàn Ọlọ́run sì bínú sí i, ó sì wí pé, “Ìwọ kò bá ti lu ilẹ̀ ní ẹẹ̀marùn-ún tàbí ní ẹ̀ẹ̀mẹfà; Nígbà náà, ìwọ kò bá ti ṣẹ́gun Ṣíríà àti pa á run pátapáta ṣùgbọ́n Nísinsìn yìí ìwọ yóò ṣẹ́gun rẹ̀ ní ẹ̀mẹ́ta péré.”