2 Ọba 13:5-11 BMY

5 Olúwa pèsè Olùgbàlà fún Ísírẹ́lì, wọ́n sì sá kúrò lọ́wọ́ agbára Ṣíríà. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Ísírẹ́lì gbé nínú ilé ara wọn gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti wà tẹ́lẹ̀.

6 Ṣùgbọ́n wọn kò yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ ilé Jéróbóámù, èyí tí ó ti fa Ísírẹ́lì láti dá. Wọ́n tẹ̀ṣíwájú nínú rẹ̀ pẹ̀lú òpó Áṣérà dúró síbẹ̀ ní Ṣamáríà.

7 Kò sí ohùn kan tí wọ́n fi sílẹ̀ ní ti ọmọ ogun Jéhóáhásì àyàfi àádọ́ta ọkùnrin ẹlẹ́ṣin, kẹ̀kẹ́ mẹ́wàá, àti ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ọmọ ogun ẹlẹ́sẹ̀, nítorí ọba Ṣíríà ti pa ìyókù run, ó sì ṣe wọ́n bí eruku nígbà pípa ọkà.

8 Fún ti ìyókù ìṣe Jéhóáhásì fún ìgbà, tí ó fi jọba, gbogbo ohun tí ó ṣe àti àṣeyọrí rẹ̀ ṣé a kò kọ wọ́n sínú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Ísírẹ́lì?

9 Jéhóáhásì sinmi pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀. A sì sin ín sí Samáríà, Jéhóásì ọmọ rẹ̀ sì rọ́pọ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.

10 Ní ọdún kẹtàdínlógójì tí Jóásì ọba Júdà, Jéhóásì ọmọ Jéhóáhásì di ọba Ísírẹ́lì ní Ṣamáríà ó sì jọba fún ọdún mẹ́rìndínlógún.

11 Ó ṣe búburú ní ojú Olúwa, kò sì yípadà kúrò nínú ọ̀kankan nínú ẹ̀ṣẹ̀ Jéróbóámù ọmọ Nébátì èyí tí ó ti ti Ísírẹ́lì láti fà. Ó sì tẹ̀síwájú nínú wọn.