11 Hírámù ọba Tírè sì rán àwọn ìránṣẹ́ sí Dáfídì, àti igi kédárì, àti àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà, àti àwọn tí ń gbẹ́ òkúta, wọ́n kọ́ ilé kan fún Dáfídì.
12 Dáfídì sì kíyèsi i pé, Olúwa ti fi ìdí òun múlẹ̀ láti jọba lórí Ísírẹ́lì, àti pé, ó gbé ìjọba rẹ̀ ga nítorí Ísírẹ́lì àwọn ènìyàn rẹ̀.
13 Dáfídì sì tún mú àwọn àlè àti aya sí i láti Jérúsálẹ́mù wá, lẹ́yìn ìgbà tí ó ti Hébírónì bọ̀: wọ́n sì bí ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin fún Dáfídì.
14 Èyí sì ni orúkọ àwọn tí a bí fún un ní Jérúsálẹ́mù; Ṣamímúà àti Sóbábù, àti Nátanì, àti Sólómónì.
15 Àti Íbéhárì, àti Élíṣúà, àti Néfégì, àti Jáfíà.
16 Àti Élíṣámà, àti Élíádà, àti Élífélétì.
17 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn Fílístínì gbọ́ pé, wọ́n ti fi Dáfídì jọba lórí Ísírẹ́lì, gbogbo àwọn Fílístínì sì gòkè wá láti wá Dáfídì; Dáfídì sì gbọ́, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìlú olódì.