10 Nítorí náà má bẹ̀rù, nítorí èmi wà pẹ̀lúù rẹ;má ṣe jẹ́ kí àyà kí ó fò ọ́, nítorí èmi ni Ọlọ́run rẹ.Èmi yóò fún ọ lókun èmi ó sì ràn ọ́ lọ́wọ́.Èmi ó gbé ọ ró pẹ̀lú ọwọ́ ọ̀tún òdodo mi.
11 “Gbogbo àwọn tí ó bínú sí ọni ojú yóò tì, tí wọn yóò sì di ẹni yẹ̀yẹ́;gbogbo àwọn tí ó lòdì sí ọyóò dàbí asán, wọn yóò ṣègbé.
12 Bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ yóò wá àwọn ọ̀ta rẹ,ìwọ kì yóò rí wọn.Gbogbo àwọn tí ó gbógun tì ọ́yóò dàbí òfuuru gbádá.
13 Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ,tí ó di ọwọ́ ọ̀tún rẹ mútí ó sì sọ fún ọ pé, má ṣe bẹ̀rù;Èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́.
14 Ìwọ má ṣe bẹ̀rù, Ìwọ Jákọ́bù kòkòrò,Ìwọ Ísírẹ́lì kékeré,nítorí Èmi fúnra mi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́,”ni Olúwa wí,olùdáǹdè rẹ, Ẹni Mímọ́ ti Ísírẹ́lì.
15 “Kíyèsi, Èmi yóò sọ ọ́ di òòlù ìpakà,tuntun tí ó mú ti eyín rẹ̀ mu, ìwọ yóò lu àwọn òkè ńlá,ìwọ yóò fọ́ wọn túútúú,a ó sì sọ òkè kékeré di ìyàngbò.
16 Ìwọ yóò fẹ́ wọn, afẹ́fẹ́ yóò sì gbá wọn mú,àti ẹ̀fúùfù yóò sì gbá wọn dànùṢùgbọ́n ìwọ yóò yọ̀ nínú Olúwaìwọ yóò sì ṣògo nínú Ẹni Mímọ́ ti Ísírẹ́lì.