22 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn kan níyìí tí a jà lóguntí a sì kó lẹ́rú,gbogbo wọn ni ó wà nínú ọ̀gbun,tàbí tí a fi pamọ́ sínú ẹ̀wọ̀n.Wọ́n ti di ìkógun,láìsí ẹnìkan tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀;wọ́n ti di ìkógun,láìsí ẹni tí yóò sọ pé, “Dá wọn padà.”
23 Ta ni nínú un yín tí yóò tẹ́tí sí èyítàbí kí ó ṣe àkíyèsí gidi ní àsìkò tí ó ń bọ̀?
24 Ta ni ó fi Jákọ́bù lélẹ̀ fún ìkógun,àti Ísírẹ́lì sílẹ̀ fún onísùnmọ̀mí?Kì í há ṣe Olúwa ni,ẹni tí àwa ti ṣẹ̀ sí?Nítorí pé wọn kò ní tẹ̀lé ọ̀nà rẹ̀;wọn kò mú òfin rẹ̀ ṣẹ.
25 Nítorí náà ni ó ṣe rọ̀jò ìbínú un rẹ̀ lé wọn lórí,rògbòdìyàn ogun.Èyí tí ó fi ahọ́n iná yí wọn po, síbẹ̀èdè kò yé wọn;ó jó wọn run, síbẹ̀ wọn kò fi sọ́kàn wọn rárá.