2 Àwọn orílẹ̀ èdè yóò rí òdodo rẹ,àti gbogbo ọba ògo rẹa ó sì máa pè ọ́ ní orúkọ mìírànèyí tí ẹnu Olúwa yóò fi fún un.
3 Ìwọ yóò sì jẹ́ adé dídán ní ọwọ́ Olúwa,adé ọba ní ọwọ́ Ọlọ́run rẹ.
4 Wọn kì yóò pè ọ́ ní ìkọ̀sílẹ̀ mọ́tàbí kí wọ́n pe ilẹ̀ rẹ ní ahoro.Ṣùgbọ́n a ó máa pè ọ́ ní Hẹfísíbà,àti ilẹ̀ rẹ ní Béúlà;nítorí Olúwa yóò yọ́nú sí ọàti ilẹ̀ rẹ ni a ó gbé níyàwó.
5 Gẹ́gẹ́ bí ọ̀dọ́mọkùrin tí í gbé ọ̀dọ́mọbìnrin níyàwóbẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọkùnrin rẹ yóò gbé ọ níyàwóGẹ́gẹ́ bí ọkọ ìyàwó ṣe é yọ̀ lórí ìyàwó rẹ̀,bẹ́ẹ̀ ni Ọlọ́run rẹ yóò yọ̀ lóríì rẹ.
6 Èmi ti fi olùṣọ́ ránṣẹ́ sórí odi rẹ ìwọ Jérúsálẹ́mù;wọn kì yóò lè dákẹ́ tọ̀sán tòru.Ẹ̀yin tí ń ké pe Olúwa,ẹ má ṣe fún ra yín ní ìsinmi,
7 àti kí ẹ má ṣe fún òun pẹ̀lú ní ìsinmitítí tí yóò fi fi ìdí Jérúsálẹ́mù múlẹ̀tí yóò sì fi òun ṣe ìyìn orí ilẹ̀ ayé.
8 Olúwa ti búra pẹ̀lú ọ̀tún rẹ̀àti nípa agbára apá rẹ:“Èmi kì yóò jẹ́ kí hóró rẹdi oúnjẹ fún ọ̀tá rẹbẹ́ẹ̀ ni àwọn àjèjì kì yóò mu wáìnìtuntun rẹ mọ́èyí tí ìwọ ti ṣe làálàá fún;