7 Èmi yóò kọ ilé mi sílẹ̀,màá fi ìní mi sílẹ̀.Èmi yóò fi ẹni tí mo fẹ́lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ lọ́wọ́.
8 Ìní mi ti dàbíkìnnìún nínú igbó sí miÓ ń bú ramúramù mọ́ mi;nítorí náà mo kórìíra rẹ̀.
9 Ìní kò ha ti dàbíẹyẹ kanna-kánnátí àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ dòyì kọ tí wọ́n sì kọjú ìjà sí i?Lọ kí o lọ ṣe àkójọ gbogbo àwọn ẹranko búburú,kó wọn wá láti wá parun.
10 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ olùṣọ́ àgùntàn ni yóò sì ba oko àjàrà mi jẹ́,tí wọn yóò sì tẹ oko mi mọ́lẹ̀;Wọ́n ó sọ oko dídára mi diibi tí a ń da ìdọ̀tí sí.
11 A ó sọ ọ́ di aṣálẹ̀ ilẹ̀tí kò wúlò níwájú mi,gbogbo ilẹ̀ ni yóò di ahoronítorí kò sí ẹnìkankan tí yóò náání.
12 Gbogbo ibi gíga tí ó wà nínú aṣálẹ̀ni àwọn apanirun ti gorí,nítorí idà Olúwa yóò paláti ìkángun kìn-ín-ní dé ìkángun ìkejì ilẹ̀ náà;kò sí ẹni tí yóò yè.
13 Àlìkámà ni wọn yóò gbìn, ṣùgbọ́n ẹ̀gún ni wọn yóò ká,wọn yóò fi ara wọn ṣe wàhálà, ṣùgbọ́n òfo ni èrè wọn.Kí ojú kí ó tìyín nítorí èrè yín,nítorí ìbínú gbígbóná Olúwa.