6 Èmi ṣọ̀kalẹ̀ lọ sí ìṣàlẹ̀ àwọn òkè ńlá;ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ìdènà rẹ̀ yí mi ká títí:ṣùgbọ́n ìwọ ti mú ẹ̀mí mi wá sókè láti inú ibú wá, Olúwa Ọlọ́run mi.
7 “Nígbà tí ó rẹ ọkàn mi nínú mi,èmi rántí rẹ, Olúwa,àdúrà mi sì wá sí ọ̀dọ̀ rẹ,nínú tẹ́ḿpìlì mímọ́ rẹ.
8 “Àwọn tí ń fàmọ́ òrìṣà èkékọ àánú ara wọn sílẹ̀.
9 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi orin ọpẹ́, rúbọ sí ọ.Èmi yóò san ẹ̀jẹ́ tí mo ti jẹ́.‘Igbàlà wá láti ọdọ Olúwa.’ ”
10 Olúwa sì pàṣẹ fún ẹja náà, ó sì pọ Jónà sí orí ilẹ̀ gbígbẹ.