9 Ẹni tí ó ní ojú àánú ni a ó bùkún fún;nítorí tí ó fi nínú oúnjẹ rẹ̀ fún olùpọ́njú.
10 Lé ẹlẹ́gàn sí ìta, ìjà yóò sì jáde;nítòótọ́ ìjà àti ẹ̀gàn yóò dẹ́kun.
11 Ẹni tí ó fẹ́ ìwà-funfun ti àyà,tí ó sì ń sọ̀rọ̀ iyì jáde, ọba yóò ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀.
12 Ojú Olúwa pa ìmọ̀ mọ́,ó sì yí ọ̀rọ̀ olùrékọjá pò.
13 Ọ̀lẹ wí pé, “Kìnnìún ń bẹ lóde!Ó pa mí ní ìgboro!”
14 Ẹnu àwọn Àṣẹ́wó obìnrín, ihò jínjìn ni;ẹni tí a ń bínú sí láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá ni yóò ṣubú sínú rẹ̀.
15 Àyà ọmọdé ni ìwà-wèrè dì sí;ṣùgbọ́n pàṣán ìtọ́ni ni yóò lé e jìnnà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.