4 Àyà mi lù, ó sì rọ bí i koríko;mo gbàgbé láti jẹ oúnjẹ mi.
5 Nítorí ohùn ìkérora mi,egungun mi lẹ̀ mọ́ ẹran ara mi.
6 Èmi dà bí ẹyẹ igún ni ijù:èmi dàbí òwìwí ibi ahoro.
7 Èmi dìde; èmí dàbí ẹyẹ lórí ilé.
8 Ní ọjọ́ gbogbo àwọn ọ̀ta ológosẹ́ mi ń gàn mí;àwọn tí ń ṣe ìkanra sí mi ń fi orúkọ mi bú.
9 Èmi jẹ eérú gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ mi, èmi si da ohun mímu mi pọ̀ pẹ̀lú omíjé.
10 Nítorí ìbínú ríru Rẹ, nítorí ìwọ ti gbé mi sókè, ìwọ sì gbé mi ṣánlẹ̀.