6 Mo gbẹ́kẹ̀lé ọ láti ìgbà ìbí mi;Ìwọ mu mi jáde láti inú ìyá mi wáèmi ó máa yìn ọ títí láé
7 Mo di ẹni ìyanu fún ọ̀pọ̀ ènìyàn,ṣùgbọ́n ìwọ ni ààbò mi tí ó lágbára.
8 Ìyìn Rẹ̀ kún ẹnu mi,o ń sọ ti ọlá Rẹ̀ ní ọjọ́ gbogbo.
9 Má ṣe ta mí nù ni ọjọ́ ogbó miMá ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ nígbà tí kò sí okun mọ́
10 Nítorí àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀ òdì sí miàwọn tí wọn dúró láti pa mí gbìmọ̀ pọ̀
11 Wọ́n wí pé, “Ọlọ́run ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀;lépa Rẹ̀ kí ẹ sì munítorí kò sí ẹni tí yóò gbà á.”
12 Má ṣe jìnnà sí mi, Ọlọ́run;wa kánkán, Ọlọ́run mi, láti rànmí lọ́wọ́.