4 Nítorí náà, òfin di ohun àìkàsí,ìdájọ́ òdodo kò sì borí.Àwọn ẹni búburú yí àwọn olódodo ká,Nítorí náà ni ìdájọ́ òdodo ṣe yí padà
5 “Ẹ wo ìnú àwọn aláìkọlà, ki ẹ sí wòye,Kí ìyàlẹnu kí o sí ṣe yin gidigidiNítorí tí èmi yóò ṣe ohun kan ni òwúrọ̀ ọjọ́ ọ yíntí ẹ̀yin kì yóò sì gbàgbọ́bí o tilẹ̀ jẹ́ pé a sọ fún un yin.
6 Nítorí pé, èmi yóò gbé àwọn ara Bábílónì dìde,àwọn aláìláàánú àti onínú fùfù ènìyàntí ó rin gbogbo ilẹ̀ ayé jáláti fi agbára gbà àwọn ibùgbé tí kì í ṣe ti wọn.
7 Wọn jẹ́ ènìyàn ti a bẹ̀rù, tí a sì páyà,ìdájọ́ wọn, àti ọláńlá wọn,Yóò máa ti inú wọn jáde.
8 Ẹ̀ṣin wọn yára ju ẹkùn lọ,wọ́n ṣì gbóná jú ìkókó àṣálẹ́ lọàwọn ẹlẹ́ṣin wọn yóò sí tan ara wọn ká;àwọn yóò sì wá láti ọ̀nà jínjìn réré,wọn yóò sí fò bí ẹyẹ igún tí ń wá láti jẹrun
9 Gbogbo wọn sì wà fún ìwà ipáìwò ojú wọn yóò sì wá síwájú;wọn sì ko ìgbékùn jọ bí i yanrìn.
10 Wọn ó si máa fí àwọn ọba ṣẹ̀ṣínwọn ó sì tún kẹ́gàn àwọn aládé.Wọn yóò sì fi gbogbo ìlú odi alágbára nì rẹ́rìnín;Nítorí pé, wọn yóò ko erùpẹ̀ jọ, wọn yóò sì gbà á