Hábákúkù 2:1-7 BMY

1 Èmi yóò dúró lórí ibùṣọ́ mi láti máa wòyeÈmi yóò sì gbé ara mi ka orí alóreÈmi yóò si ṣọ́ láti gbọ́ ohun tí yóò sọ fún nuàti èsì ti èmi yóò fún ẹ̀sùn yìí nígbà tó bá ń bá mi wí;

2 Nígbà náà ni Olúwa dáhun pé:“Kọ ìṣípayá náa sílẹ̀kí o sí han ketekete lórí wàláàkí ẹni tí ń kà á, lè máa sáré.

3 Nítorí ìṣípayá náà jẹ́ tí ìgbà kan tí a múra sílẹ̀ dè;yóò máa yára sí ìgbẹ̀yinkí yóò sí sọ èkébí o tilẹ̀ lọ́ra, dúró dè é;nítorí, dájúdájú, yóò dé, kí yóò sí pẹ́”

4 “Kíyèsí, ọkàn rẹ tí ó gbéga;Ìfẹ́ rẹ̀ kò dúró ṣinṣin nínú rẹ̀,ṣùgbọ́n olododo yóò wa nípa ìgbàgbọ́ rẹ̀.

5 Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lú, nítorí tí ọtí-wáìnì ni ẹ̀tàn,agbéraga ènìyàn òun, kò sì ní sinmiẹni tí ó sọ ìfá rẹ di gbígbòòrò bí ipò-òkú,ó sì dàbí ikú, a kò sì le tẹ́ ẹ lọ́rùn,ó kó gbogbo orílẹ̀-èdè jọ sí ọ̀dọ̀ó sì gba gbogbo ènìyàn jọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀.

6 “Gbogbo àwọn wọ̀nyí kì yóò máa pa òwe sí i tí wọn yóò sì máa kọ orin òwe sí i wí pé,“ ‘Ègbé ni fún ẹni tí ń mu ohun tí kì í ṣe tirẹ̀ pọ̀ sí i!Tí ó sì ṣọ ara rẹ̀ di ọlọ́rọ̀ nípaṣẹ̀ ìlọ́nilọ́wọ́ gbà!Eléyìí yóò ha ti pẹ́ tó?’

7 Ǹjẹ́ ẹni ti ó yọ ọ́ lẹ́nu, kí yóò ha dìde lójijì?Àti àwọn tí ó wàhálà rẹ kì yóò ha jí ni bi?Nígbà náà ni ìwọ yóò wa dí ìkógun fún wọn.