1 Ní ìparí, ará, a sọ fún un yín bí ẹ ti ń gbé láti wu Ọlọ́run, àní gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí ń ṣe. Nísinsìnyìí, a bèèrè, a sì ń rọ̀ yín nínú Jésù Olúwa láti ṣe bẹ́ẹ̀ àti bẹ́ẹ̀ sí.
2 Nítorí pé, ẹyin mọ àṣẹ tí a pa fún yín láti ọ̀dọ̀ Olúwa Jésù.
3 Nítorí ìfẹ́ Ọlọ́run ni pé kí ẹ jẹ́ mímọ, kí ẹ sì yàgò kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ àgbérè,
4 kí ẹnikọ̀ọ̀kan yín kọ́ láti sàkóso ara rẹ̀ ní ọ̀nà mímọ́ àti pẹ̀lú ọlá,
5 kì í ṣe ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn aláìkọlà, ẹni tí kò mọ Ọlọ́run;