19 Ẹ má ṣe pa iná Ẹ̀mí Mímọ́.
20 Ẹ má ṣe kẹ́gàn àwọn ti ń ìsọtẹ́lẹ̀.
21 Ṣùgbọ́n ẹ dán gbogbo nǹkan wò. Ẹ di èyí tí ṣe òtítọ́ mú.
22 Ẹ yẹra fún ohunkóhun tí í ṣe ibi.
23 Kí Ọlọ́run àlàáfíà pàápàá wẹ̀ yín mọ́, kí ó sì yà yín sọ́tọ̀ fún ara rẹ̀. Kí Ọlọ́run pa ẹ̀mí àti ọkàn pẹ̀lú ara yín mọ́, títí di ìgbà wíwá Jésù Kírísítì Olúwa wa.
24 Olótítọ́ ni ẹni tí ó pè yín, yóò sì ṣe.
25 Ẹ̀yin ará, ẹ gbàdúrà fún wa.