15 Nítorí àwọn mìíràn ti yípadà kúrò sí ẹ̀yìn Sàtánì.
16 Bí ọkùnrin tàbí obìnrin kan tí ó gbàgbọ́ bá ní àwọn opó, kí ó máa ràn wọ́n lọ́wọ́, kí a má sì di ẹrù lé ìjọ, kí wọn lè máa ran àwọn ti í ṣe opó nítòótọ́ lọ́wọ́.
17 Àwọn alàgbà ti ó ṣe àkóso dáradára ni kí a kà yẹ sí ọlá ìlọ́po méjì, pẹ̀lu pẹ̀lú àwọn ti ó ṣe làálàá ni ọ̀rọ̀ àti ni kíkọ́ni.
18 Nítorí tí Ìwé-Mímọ́ wí pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ di màlúù ti ń tẹ ọkà lẹnu.” Àti pé, “ọ̀yà alágbàse tọ́ sí i.”
19 Má ṣe gba ẹ̀sùn sí alàgbà kan, bí kò ṣe láti ẹnu ẹlẹ́rìí méjì-mẹ́ta.
20 Bá àwọn tí ó ṣẹ̀ wí níwájú gbogbo ènìyàn, kí àwọn ìyókù pẹ̀lú bà á lè bẹ̀rù.
21 Mo pàṣẹ fún ọ níwájú Ọlọ́run, àti Kírísítì Jésù, àti àwọn ańgẹ́lì àyànfẹ́ kí ìwọ máa ṣakíyèsí nǹkan wọ̀nyí, láìṣe ojúṣàájú, láti fi ègbè ṣe ohunkóhun.