1 Ọ̀rọ̀ tí OLUWA sọ fún Mika, ará Moreṣeti nípa Jerusalẹmu ati Samaria nìyí, ní àkókò ìjọba Jotamu, ati ti Ahasi ati ti Hesekaya, àwọn ọba Juda.
2 Ẹ gbọ́, gbogbo ẹ̀yin orílẹ̀-èdè,fetí sílẹ̀, ìwọ ayé, ati gbogbo ohun tí ó wà ninu rẹ̀.Kí OLUWA fúnrarẹ̀ jẹ́ ẹlẹ́rìí tí yóo takò yín,àní OLUWA, láti inú tẹmpili rẹ̀ mímọ́.
3 Wò ó, OLUWA ń jáde bọ̀ láti inú ilé rẹ̀,yóo sọ̀kalẹ̀, yóo sì rìn lórí àwọn òkè gíga ayé.
4 Àwọn òkè ńlá yóo yọ́ lábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀, bí ìda tíí yọ̀ níwájú iná;àwọn àfonífojì yóo pínyàgẹ́gẹ́ bí omi tí a dà sílẹ̀ ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè.