Ẹkún Jeremáyà 2:2-8 BMY

2 Làìní àánú ni Olúwa gbéibùgbé Jákọ́bù mì;nínú ìrunú rẹ̀ ni ó wóibi gíga ọmọbìnrin Júdà lulẹ̀.Ó ti mú ìjọba àti àwọn ọmọ aládé ọkùnrinlọ sínú ilẹ̀ ní àìlọ́wọ̀.

3 Ní ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó kégbogbo ìwo Ísírẹ́lì.Ó ti mú ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ kúrònígbà tí àwọn ọ̀tá dé.Ó run ní Jákọ́bù bí ọ̀wọ́ inání àgọ́ àwọn ọmọbìnrin Síónì.

4 Ó na ọfà rẹ̀ bí ọtá;ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ sì múraBí ti ọ̀ta tí ó ti parunó tú ìbínú rẹ̀ jáde bí inásórí àgọ́ ọmọbìnrin Síónì.

5 Olúwa dà bí ọ̀tá;ó gbé Ísírẹ́lì mì.Ó ti gbé gbogbo ààfin rẹ̀ mìó pa ibi gíga rẹ̀ run.Ó sọ ìmí ẹ̀dùn àti ìbànújẹ́ di púpọ̀fún àwọn ọmọbìnrin Júdà.

6 Ó mú ìparun bá ibimímọ́,ó pa ibi ìpàdé rẹ̀ run. Olúwa ti mú Síónì gbàgbéọjọ́ àṣè àti ọ̀ṣẹ̀ tí ó yàn;nínú ìbínú gbígbóná rẹ̀ ni ó runọba àti olórí àlùfáà.

7 Olúwa ti kọ̀ pẹpẹ rẹ̀ sílẹ̀ó sì ti kọ̀ ibi mímọ́ rẹ̀.Ó sì fi lé ọ̀ta lọ́wọ́àwọn odi ààfin rẹ̀;wọ́n sì kígbe ní ilé Olúwagẹ́gẹ́ bí ọjọ́ ìpèjẹ tí a yàn.

8 Olúwa pinnu láti faògiri tí ó yí ọmọbìnrin Síónì ya.Ó gbé wọn sórí òṣùnwọ̀n,kò sì fa ọwọ́ rẹ̀ padà kúrò nínú ìparun wọn.Ó mú kí ilé-ìsọ́ àti odi rẹ̀ sọ̀fọ̀wọ́n ṣòfò papọ̀.