7 Ọmọ ọba ọkùnrin wọn mọ́ ju òjò dídì,wọ́n sì funfun ju wàrà lọlára, wọ́n ni ìtọ́jú bí iyùn pupa,ìrísí wọn dàbí sáfírè.
8 Ṣùgbọ́n nísinsìn yìí wọ́n dúdú ju èédú;wọn kò sì dá wọn mọ̀ ní òpópó.Ara wọn hun mọ́ egungun;ó sì gbẹ bí igi gbígbẹ.
9 Àwọn tí ó kù nípasẹ̀ idà sànju àwọn tí ìyàn pa;tí ó wọ àkísà ebi, tí ó ń ṣòfòfún àìní oúnjẹ láti inú pápá.
10 Pẹ̀lú ọwọ́ àwọn obìnrin aláàánúni wọ́n ṣe ọmọ wọntí ó di oúnjẹ fún wọnnígbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run.
11 Olúwa ti fi ihò kíkún fún ìbínú rẹ̀;ó sì tú ìbínú gbígbóná rẹ̀ jáde.Ó da iná ní Síónìtí ó jó ìpìlẹ̀ rẹ̀ run.
12 Àwọn ọba ayé kò gbàgbọ́,tàbí àwọn ènìyàn ayé,wí pé àwọn ọ̀tá àti aninilára le wọodi ìlú Jérúsálẹ́mù.
13 Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn wòlíìàti àìṣedédé àwọn olórí àlùfáà,tí ó ta ẹ̀jẹ̀ àwọn olódodosílẹ̀ láàrin rẹ̀.