Ẹkún Jeremaya 1:3-9 BM

3 Juda ti lọ sí ìgbèkùn,wọ́n sì ń fi tipátipá mú un sìn.Nisinsinyii, ó ń gbéààrin àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn,kò sì ní ibi ìsinmi.Ọwọ́ àwọn tí wọn ń lépa rẹ̀ ti tẹ̀ ẹ́,ninu ìdààmú rẹ̀.

4 Àwọn ọ̀nà tó lọ sí Sioni ń ṣe ìdárò,nítorí kò sí ẹni tí ó ń gba ibẹ̀ lọsíbi àwọn àjọ̀dún tí a yà sọ́tọ̀ mọ́.Àwọn ẹnubodè rẹ̀ ti di ahoro,àwọn alufaa rẹ̀ sì ń kẹ́dùn.Wọ́n ń pọ́n àwọn ọmọbinrin rẹ̀ lójú,òun pàápàá sì ń joró lọpọlọpọ.

5 Àwọn ọ̀tá ilẹ̀ Juda ti borí rẹ̀, wọ́n ti wá di ọ̀gá rẹ̀,nítorí pé, OLUWA ń jẹ ẹ́ níyà fún ọpọlọpọ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀,àwọn ọ̀tá ti ti àwọn ọmọ rẹ̀ ṣáájú,wọ́n ti kó wọn nígbèkùn lọ.

6 Gbogbo ògo Jerusalẹmu ti fò lọ kúrò lára rẹ̀,àwọn olórí rẹ̀ dàbí àgbọ̀nríntí kò rí koríko tútù jẹ;agbára kò sí fún wọn mọ́,wọ́n ń sálọ níwájú àwọn tí ń lé wọn.

7 Ní ọjọ́ ìpọ́njú ati ìbànújẹ́,Jerusalẹmu ranti àwọn nǹkan iyebíye tí ó ní ní ìgbà àtijọ́.Nígbà tí àwọn eniyan rẹ̀ bọ́ sọ́wọ́ ọ̀tá,tí kò sì sí ẹni tí yóo ràn wọ́n lọ́wọ́.Àwọn ọ̀tá bẹ̀rẹ̀ sí yọ̀ ọ́,wọ́n sì ń fi ṣẹ̀sín nítorí ìṣubú rẹ̀.

8 Jerusalẹmu ti dẹ́ṣẹ̀ burúkú,nítorí náà ó ti di eléèérí.Àwọn tí wọn ń bu ọlá fún un tẹ́lẹ̀ ti ń kẹ́gàn rẹ̀,nítorí pé wọ́n ti rí ìhòòhò rẹ̀.Òun pàápàá ń kérora, ó sì fi ojú pamọ́.

9 Ìwà èérí rẹ̀ hàn níbi ìṣẹ́tí aṣọ rẹ̀,kò sì bìkítà fún ìparun tí ń bọ̀.Nítorí náà ni ìṣubú rẹ̀ fi pọ̀, tí kò sì fi ní olùtùnú.Ó ké pe OLUWA pé kí ó ṣíjú wo ìnira òun,nítorí pé ọ̀tá ti borí rẹ̀.