21 Ṣugbọn mo tún ń ranti nǹkankan,mo sì ní ìrètí.
22 Nítorí pé Ìfẹ́ OLUWA tí kì í yẹ̀ kò nípẹ̀kun,àánú rẹ̀ kò sì lópin;
23 ọ̀tun ni wọ́n láràárọ̀,òtítọ́ rẹ̀ pọ̀.
24 Ọkàn mi wí pé, “OLUWA ni ìpín mi,nítorí náà lọ́dọ̀ rẹ̀ ni ìrètí mi wà.”
25 OLUWA a máa ṣe oore fún àwọn tí wọn dúró dè é,tí wọn sì ń wá ojurere rẹ̀.
26 Ó dára kí eniyan dúró jẹ́ẹ́, de ìgbàlà OLUWA.
27 Ó dára kí eniyan foríti àjàgà ìtọ́sọ́nà ní ìgbà èwe.