10 “Nítorí ìwà ìkà tí ẹ hù sí àwọn ọmọ Israẹli, arakunrin yín,ojú yóo tì yína óo sì pa yín run títí lae.
11 Ní ọjọ́ tí àwọn ọ̀tá ń kó ọrọ̀ wọn lọ,tí àwọn àjèjì wọ inú ìlú wọn,tí àwọn ọ̀tá sì ń ṣẹ́ gègé lórí Jerusalẹmu,ẹ dúró, ẹ̀ ń wò wọ́n;ẹ sì dàbí ọ̀kan ninu wọn.
12 O kì bá tí fi arakunrin rẹ ṣẹ̀sínní ọjọ́ ìpọ́njú rẹ̀;o kì bá tí jẹ́ kí inú rẹ dùn,ní ọjọ́ ìparun àwọn eniyan Juda;o kì bá tí fọ́nnu ní ọjọ́ ìbànújẹ́ wọn.
13 O kì bá tí wọ ìlú àwọn eniyan miní ọjọ́ ìpọ́njú wọn;o kì bá tí fi wọ́n ṣẹ̀sínní ọjọ́ àjálù wọn;o kì bá tí kó wọn lẹ́rùní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.
14 O kì bá tí dúró sí oríta,kí o máa mú àwọn tí wọn ń gbìyànjú láti sá àsálà;o kì bá tí fà wọ́n lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.
15 “Ọjọ́ ìdájọ́ OLUWA fẹ́rẹ̀ dé sórí àwọn orílẹ̀-èdè;a óo san án fún ọ, gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.Ohun tí o bá ṣe, yóo pada sí orí ara rẹ.
16 Ẹ̀yin eniyan mi, bí ẹ ti jìyà ní òkè mímọ́ mi,bẹ́ẹ̀ ni gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè náà yóo jìyà;wọn óo jìyà yóo tẹ́ wọn lọ́rùn,wọn yóo sì wà gẹ́gẹ́ bí ẹni pé wọn kò sí rí.