11 Ní ọjọ́ tí àwọn ọ̀tá ń kó ọrọ̀ wọn lọ,tí àwọn àjèjì wọ inú ìlú wọn,tí àwọn ọ̀tá sì ń ṣẹ́ gègé lórí Jerusalẹmu,ẹ dúró, ẹ̀ ń wò wọ́n;ẹ sì dàbí ọ̀kan ninu wọn.
12 O kì bá tí fi arakunrin rẹ ṣẹ̀sínní ọjọ́ ìpọ́njú rẹ̀;o kì bá tí jẹ́ kí inú rẹ dùn,ní ọjọ́ ìparun àwọn eniyan Juda;o kì bá tí fọ́nnu ní ọjọ́ ìbànújẹ́ wọn.
13 O kì bá tí wọ ìlú àwọn eniyan miní ọjọ́ ìpọ́njú wọn;o kì bá tí fi wọ́n ṣẹ̀sínní ọjọ́ àjálù wọn;o kì bá tí kó wọn lẹ́rùní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.
14 O kì bá tí dúró sí oríta,kí o máa mú àwọn tí wọn ń gbìyànjú láti sá àsálà;o kì bá tí fà wọ́n lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.
15 “Ọjọ́ ìdájọ́ OLUWA fẹ́rẹ̀ dé sórí àwọn orílẹ̀-èdè;a óo san án fún ọ, gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.Ohun tí o bá ṣe, yóo pada sí orí ara rẹ.
16 Ẹ̀yin eniyan mi, bí ẹ ti jìyà ní òkè mímọ́ mi,bẹ́ẹ̀ ni gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè náà yóo jìyà;wọn óo jìyà yóo tẹ́ wọn lọ́rùn,wọn yóo sì wà gẹ́gẹ́ bí ẹni pé wọn kò sí rí.
17 “Ṣugbọn ní òkè Sionini àwọn tí wọ́n bá sá àsálà yóo máa gbé,yóo sì jẹ́ òkè mímọ́;àwọn ọmọ Jakọbu yóo gba ohun ìní wọn pada.