Ọbadaya 1:14-20 BM

14 O kì bá tí dúró sí oríta,kí o máa mú àwọn tí wọn ń gbìyànjú láti sá àsálà;o kì bá tí fà wọ́n lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́ní ọjọ́ ìpọ́njú wọn.

15 “Ọjọ́ ìdájọ́ OLUWA fẹ́rẹ̀ dé sórí àwọn orílẹ̀-èdè;a óo san án fún ọ, gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.Ohun tí o bá ṣe, yóo pada sí orí ara rẹ.

16 Ẹ̀yin eniyan mi, bí ẹ ti jìyà ní òkè mímọ́ mi,bẹ́ẹ̀ ni gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè náà yóo jìyà;wọn óo jìyà yóo tẹ́ wọn lọ́rùn,wọn yóo sì wà gẹ́gẹ́ bí ẹni pé wọn kò sí rí.

17 “Ṣugbọn ní òkè Sionini àwọn tí wọ́n bá sá àsálà yóo máa gbé,yóo sì jẹ́ òkè mímọ́;àwọn ọmọ Jakọbu yóo gba ohun ìní wọn pada.

18 Ilé Jakọbu yóo dàbí iná,ilé Josẹfu yóo dàbí ọ̀wọ́ iná,ilé Esau yóo sì dàbí àgékù koríko.Wọn yóo jó ilé Esau;àwọn ìran Esau yóo jó àjórun láìku ẹnìkan;nítorí pé OLUWA ló sọ bẹ́ẹ̀.

19 Àwọn tí wọn ń gbé Nẹgẹbu yóo gba òkè Edomu,àwọn tí wọ́n wà ní ẹsẹ̀ Ṣefelayóo gba ilẹ̀ àwọn ará Filistia;wọn yóo gba gbogbo agbègbè Efuraimu ati ilẹ̀ Samaria,àwọn ará Bẹnjamini yóo sì gba ilẹ̀ Gileadi.

20 Àwọn ọmọ Israẹlití wọ́n wà ní oko ẹrú ní ilẹ̀ Halawọ́n óo gba ilẹ̀ Fonike títí dé Sarefati;àwọn eniyan Jerusalẹmu tí wọ́n wà ní oko ẹrú ní ilẹ̀ Sefaradiyóo gba àwọn ìlú tí ó wà ní Nẹgẹbu.