Sakaraya 10:1-7 BM

1 Ẹ bèèrè òjò lọ́wọ́ OLUWA ní àkókò rẹ̀, àní lọ́wọ́ OLUWA tí ó dá ìṣúdẹ̀dẹ̀ òjò; Òun ló ń fún eniyan ní ọ̀wààrà òjò, tí àwọn ohun ọ̀gbìn fi ń tutù yọ̀yọ̀.

2 Ìsọkúsọ ni àwọn ère ń sọ, àwọn aríran ń ríran èké; àwọn tí ń lá àlá ń rọ́ àlá irọ́, wọ́n sì ń tu àwọn eniyan ninu lórí òfo. Nítorí náà ni àwọn eniyan fi ń rìn káàkiri bí aguntan tí kò ní olùṣọ́.

3 OLUWA ní, “Inú mi ru sí àwọn olùṣọ́-aguntan, n óo sì fìyà jẹ àwọn alákòóso. Nítorí èmi OLUWA àwọn ọmọ ogun ń tọ́jú agbo mi, àní àwọn eniyan Juda, wọn yóo sì dàbí ẹṣin alágbára lójú ogun.

4 Ninu wọn ni a óo ti rí òkúta igun ilé, tí a lè pè ní olórí, aṣaaju, ati aláṣẹ, láti ṣe àkóso àwọn eniyan mi.

5 Gbogbo wọn óo jẹ́ akikanju lójú ogun, wọn óo tẹ àwọn ọ̀tá wọn mọ́lẹ̀ ní ìgboro; wọn óo jagun, nítorí OLUWA wà pẹlu wọn, wọn óo sì dá àyà já àwọn tí wọn ń gun ẹṣin.

6 “N óo sọ ilé Juda di alágbára,n óo sì gba ilé Josẹfu là.N óo mú wọn pada,nítorí àánú wọn ń ṣe mí,wọn yóo dàbí ẹni pé n kò kọ̀ wọ́n sílẹ̀ rí;nítorí èmi ni OLUWA Ọlọrun wọn,n óo sì gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ wọn.

7 Nígbà tó bá yá, ilé Efuraimu yóo dàbí jagunjagun alágbára,inú wọn yóo sì dùnbí inú ẹni tí ó mu ọtí waini.Nígbà tí àwọn ọmọ wọn bá rí i,inú wọn yóo dùn,ọkàn wọn yóo sì yin OLUWA.