20 Mo fi Ọlọrun jẹ́rìí pé kò sí irọ́ ninu ohun tí mò ń kọ si yín yìí!
21 Lẹ́yìn náà mo lọ sí agbègbè Siria ati ti Silisia.
22 Àwọn ìjọ Kristi tí ó wà ní Judia kò mọ̀ mí sójú.
23 Ṣugbọn wọ́n ń gbọ́ pé, “Ẹni tí ó ti ń fìtínà wa tẹ́lẹ̀ rí ti ń waasu ìyìn rere igbagbọ tí ó fẹ́ parun nígbà kan rí.”
24 Wọ́n bá ń yin Ọlọrun lógo nítorí mi.