Ẹkún Jeremáyà 2:7-13 BMY

7 Olúwa ti kọ̀ pẹpẹ rẹ̀ sílẹ̀ó sì ti kọ̀ ibi mímọ́ rẹ̀.Ó sì fi lé ọ̀ta lọ́wọ́àwọn odi ààfin rẹ̀;wọ́n sì kígbe ní ilé Olúwagẹ́gẹ́ bí ọjọ́ ìpèjẹ tí a yàn.

8 Olúwa pinnu láti faògiri tí ó yí ọmọbìnrin Síónì ya.Ó gbé wọn sórí òṣùnwọ̀n,kò sì fa ọwọ́ rẹ̀ padà kúrò nínú ìparun wọn.Ó mú kí ilé-ìsọ́ àti odi rẹ̀ sọ̀fọ̀wọ́n ṣòfò papọ̀.

9 Ẹnu ọ̀nà rẹ̀ ti wọ inú ilẹ̀;òpó rẹ̀ ni ó wó tí ó sì ti bàjẹ́.Ọba àti ọmọ ọbakùnrin rẹ̀ wà ní ìgbèkùn láàrin àwọn orílẹ̀ èdè,kò sí òfin mọ́,àwọn wòlíì rẹ̀ kò ríìran láti ọ̀dọ̀ Olúwa mọ́.

10 Àwọn àgbààgbà ọmọbìnrin Síónìjókòó sílẹ̀ ní ìdákẹ́rọ́rọ́;wọ́n da eruku sí orí wọnwọ́n sì wọ aṣọ àkísà.Àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Jérúsálẹ́mùti tẹrí wọn ba sí ilẹ̀.

11 Ojú mi kọ̀ láti sunkún,mo ń jẹ ìrora nínú mi,mo tú ọkàn mi jáde sí ilẹ̀nítorí a pa àwọn ènìyàn mí run,nítorí àwọn ọmọdé àti ọmọ ọwọ́ ń kúní òpópó ìlú.

12 Wọ́n wí fún àwọn ìyá wọn,“Níbo ni àkàrà àti wáìnì wà?” Wò óbí wọ́n ṣe ń kú lọ bí àwọn ọkùnrin tí a ṣe léṣení àwọn òpópónà ìlú,bí ayé wọn ṣe ń ṣòfòláti ọwọ́ ìyá wọn.

13 Kí ni mo le sọ fún ọ?Pẹ̀lú u kí ni mo lè fi ọ́ wé,Ìwọ ọmọbìnrin Jérúsálẹ́mù?Kí sì ni mo lè fi ọ́ wé,kí n lè tù ọ́ nínú,Ìwọ wúndíá bìnrin Síónì?Ọgbẹ́ rẹ jìn bí òkun.Ta ni yóò wò ọ́ sàn?