Ẹkún Jeremáyà 2:9-15 BMY

9 Ẹnu ọ̀nà rẹ̀ ti wọ inú ilẹ̀;òpó rẹ̀ ni ó wó tí ó sì ti bàjẹ́.Ọba àti ọmọ ọbakùnrin rẹ̀ wà ní ìgbèkùn láàrin àwọn orílẹ̀ èdè,kò sí òfin mọ́,àwọn wòlíì rẹ̀ kò ríìran láti ọ̀dọ̀ Olúwa mọ́.

10 Àwọn àgbààgbà ọmọbìnrin Síónìjókòó sílẹ̀ ní ìdákẹ́rọ́rọ́;wọ́n da eruku sí orí wọnwọ́n sì wọ aṣọ àkísà.Àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin Jérúsálẹ́mùti tẹrí wọn ba sí ilẹ̀.

11 Ojú mi kọ̀ láti sunkún,mo ń jẹ ìrora nínú mi,mo tú ọkàn mi jáde sí ilẹ̀nítorí a pa àwọn ènìyàn mí run,nítorí àwọn ọmọdé àti ọmọ ọwọ́ ń kúní òpópó ìlú.

12 Wọ́n wí fún àwọn ìyá wọn,“Níbo ni àkàrà àti wáìnì wà?” Wò óbí wọ́n ṣe ń kú lọ bí àwọn ọkùnrin tí a ṣe léṣení àwọn òpópónà ìlú,bí ayé wọn ṣe ń ṣòfòláti ọwọ́ ìyá wọn.

13 Kí ni mo le sọ fún ọ?Pẹ̀lú u kí ni mo lè fi ọ́ wé,Ìwọ ọmọbìnrin Jérúsálẹ́mù?Kí sì ni mo lè fi ọ́ wé,kí n lè tù ọ́ nínú,Ìwọ wúndíá bìnrin Síónì?Ọgbẹ́ rẹ jìn bí òkun.Ta ni yóò wò ọ́ sàn?

14 Ìran àwọn wòlíì rẹjẹ́ kìkì ẹ̀tàn láìní ìwọ̀n;wọn kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ hàntí yóò mú ìgbèkùn kúrò fún ọ.Àwọn òrìṣà tí wọ́n fún ọjẹ́ èké àti ìsìnà.

15 Àwọn tí ó gba ọ̀nà ọ̀dọ̀ rẹpàtẹ́wọ́ lé ọ lórí;wọ́n kẹ́gàn wọ́n ju orí wọnsí ọmọbìnrin Jérúsálẹ́mù:“Èyí ha ni ìlú tí à ń pè níàṣepé ẹwà,ìdùnnú gbogbo ayé?”