7 Rere ni Olúwa,ààbò ní ọjọ ìpọ́njú.Òun sì tọ́jú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀ lé e,
8 Ṣùgbọn pẹ̀lú ìkún omi ńlání òun yóò fi ṣe ìparun ibẹ̀ dé òpin;òkùnkùn yóò sì máa lépa àwọn ọ̀tá rẹ̀.
9 Kí ni ẹ̀yìn ń gbìmọ lòdì sí Olúwa?Òun yóò fi òpin sí i,Ìpọ́njú kì yóò wáyé ní ìgbà kejì
10 Wọn yóò sì lọ́lù papọ̀ bí ẹ̀gún òṣùṣùwọn yóò sì mu àmupara nínú ọtí wáìnì wọna ó sì run wọn gẹ́gẹ́ bi àkékù koríko gbígbẹ
11 Láti ọ̀dọ̀ rẹ, ìwọ Nínéfè, ni ẹnìkan ti jáde wátí ó ń gbérò ibi sí Olúwati ó sì ń gbìmọ̀ búburú.
12 Báyìí ni Olúwa wí:“Bí wọ́n tilẹ̀ pé, tí wọ́n sì pọ̀ níye,Ṣùgbọ́n, báyìí ní a ó ké wọn lulẹ̀,nígbà tí òun ó bá kọ́já.Bí mo tilẹ̀ ti pọ́n ọ lójú ìwọ Júdà, èmi kì yóò pọ́n ọ lójú mọ́.
13 Nísinsin yìí ni èmi yóò já àjàgà wọn kúrò ní ọrùn rẹèmi yóò já sẹkẹ́sẹkẹ̀ rẹ dànù.”