1 Pọ́ọ̀lù Àpósítélì Jésù Kírisítì nípa ìfẹ́ Ọlọ́run, àti Tímótíù arákùnrin wá, sí ìjọ Ọlọ́run tí ó wà ní Kọ́ríńtí pẹ̀lú gbogbo àwọn ènìyàn-mímọ́ tí ó wà ní gbogbo Ákáyà:
2 Oore-ọ̀fẹ́ si yín àti àlàáfíà làti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa, àti Jésù Kírísítì Olúwa.
3 Olùbùkún ni Ọlọ́run, àti Baba Jésù Kírísítì Olúwa wa, Baba ìyọ́nú, àti Ọlọ́run ìtùnú gbogbo;
4 Ẹni tí ń tù wá nínú ni gbogbo ìdààmú wa, ki àwa lè máa pẹ̀lú tu àwọn tí ó wá nínú ìdààmú nínú, nípá ìtùnú náà ti a fi ń tú àwa fúnra wa nínú làti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá.
5 Nítorí pé bí ìjìyà Kírísítì ti sínú ayé wa,, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ nì ìtùnú wa dí púpọ pẹ̀lú nípa Kírísítì.