Ẹkún Jeremaya 2:10-16 BM

10 Àwọn àgbààgbà Sioni jókòó lórí ilẹ̀, wọ́n dákẹ́ rọ́rọ́,wọ́n ku eruku sórí,wọ́n sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀.Àwọn ọmọbinrin Jerusalẹmu doríkodò.

11 Ẹkún sísun ti sọ ojú mi di bàìbàì,ìdààmú bá ọkàn mi;ìbànújẹ́ sì mú kí ó rẹ̀wẹ̀sìnítorí ìparun àwọn eniyan mi,nítorí pé àwọn ọmọ wẹ́wẹ́ati àwọn ọmọ ọwọ́ ń dákú lójú pópó láàrin ìlú.

12 Bí wọ́n ti ń dákú láàrin ìlú,bí ẹni tí a ṣá lọ́gbẹ́,tí wọ́n sì ń kú lọ lẹ́yìn ìyá wọn,wọ́n ń sọkún sí àwọn ìyá wọn pé:“Ebi ń pa wá, òùngbẹ sì ń gbẹ wá.”

13 Kí ni mo lè sọ nípa rẹ,kí sì ni ǹ bá fi ọ́ wé, Jerusalẹmu?Kí ni mo lè fi wé ọ,kí n lè tù ọ́ ninu, ìwọ Sioni?Nítorí bí omi òkun ni ìparun rẹ gbòòrò;ta ló lè mú ọ pada bọ̀ sípò?

14 Ìran èké ati ti ẹ̀tàn ni àwọn wolii rẹ ń rí sí ọ;wọn kò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn ọ́,kí wọ́n lè dá ire rẹ pada,ṣugbọn wọ́n ń ríran èké ati ìran ẹ̀tàn sí ọ.

15 Gbogbo àwọn tí ń rékọjá lọń pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí,wọ́n ń pòṣé,wọ́n sì ń mi orí wọn sí ọ, Jerusalẹmu.Wọ́n ń sọ pé:“Ṣé ìlú yìí ni à ń pè níìlú tí ó lẹ́wà jùlọ,tí ó jẹ́ ayọ̀ gbogbo ayé?”

16 Gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ ń fi ọ́ ṣẹ̀sín,wọ́n ń pòṣé,wọ́n ń fi ọ́ ṣe ẹlẹ́yà.Wọ́n ń wí pé:“A ti pa á run!Ọjọ́ tí a tí ń retí nìyí;ọwọ́ wa ti tẹ Jerusalẹmu wàyí!A ti rí ohun tí à ń wá!”