Ẹkún Jeremaya 2:14-20 BM

14 Ìran èké ati ti ẹ̀tàn ni àwọn wolii rẹ ń rí sí ọ;wọn kò fi ẹ̀ṣẹ̀ rẹ hàn ọ́,kí wọ́n lè dá ire rẹ pada,ṣugbọn wọ́n ń ríran èké ati ìran ẹ̀tàn sí ọ.

15 Gbogbo àwọn tí ń rékọjá lọń pàtẹ́wọ́ lé ọ lórí,wọ́n ń pòṣé,wọ́n sì ń mi orí wọn sí ọ, Jerusalẹmu.Wọ́n ń sọ pé:“Ṣé ìlú yìí ni à ń pè níìlú tí ó lẹ́wà jùlọ,tí ó jẹ́ ayọ̀ gbogbo ayé?”

16 Gbogbo àwọn ọ̀tá rẹ ń fi ọ́ ṣẹ̀sín,wọ́n ń pòṣé,wọ́n ń fi ọ́ ṣe ẹlẹ́yà.Wọ́n ń wí pé:“A ti pa á run!Ọjọ́ tí a tí ń retí nìyí;ọwọ́ wa ti tẹ Jerusalẹmu wàyí!A ti rí ohun tí à ń wá!”

17 OLUWA ti ṣe bí ó ti pinnu,ó ti mú ìlérí rẹ̀ ṣẹ,bí ó ti sọ ní ìgbà àtijọ́.Ó ti wó ọ lulẹ̀ láìṣàánú rẹ;ó ti jẹ́ kí ọ̀tá yọ̀ ọ́,ó ti fún àwọn ọ̀tá rẹ ni agbára kún agbára.

18 Ẹ kígbe sí OLUWA,ẹ̀yin ará Sioni!Ẹ jẹ́ kí omi máa dà lójú yín pòròpòrò tọ̀sán-tòru;ẹ má sinmi,ẹ má sì jẹ́ kí oorun kùn yín.

19 Ẹ dìde, ẹ kígbe lálẹ́,ní àkókò tí àwọn aṣọ́de ń bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́!Ẹ tú ẹ̀dùn ọkàn yín jáde bí omi níwájú OLUWA!Ẹ gbé ọwọ́ ẹ̀bẹ̀ sókè sí i,nítorí ẹ̀mí àwọn ọmọ yín tí ebi ń pa kú lọ ní gbogbo ìkóríta.

20 Wò ó! OLUWA,ṣe akiyesi ohun tí ń ṣẹlẹ̀!Wo àwọn tí ò ń ṣe irú èyí sí!Ṣé ó yẹ kí àwọn obinrin máa jẹ ọmọ wọn?Ọmọ ọwọ́ tí wọn ń tọ́jú!Ṣé ó yẹ kí á pa alufaa ati wolii, ní ibi mímọ́ OLUWA?