Sakaraya 9:9-15 BM

9 Ẹ máa yọ̀, ẹ̀yin ará Sioni!Ẹ hó ìhó ayọ̀, ẹ̀yin ará Jerusalẹmu!Wò ó! Ọba yín ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ yín;ajagun-ṣẹ́gun ni,sibẹsibẹ ó jẹ́ onírẹ̀lẹ̀, ó sì gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́,kódà, ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ni ó gùn.

10 OLUWA ní, òun óo kó kẹ̀kẹ́ ogun kúrò ní Efuraimu,òun óo kó ẹṣin ogun kúrò ní Jerusalẹmu,a óo sì ṣẹ́ ọfà ogun.Yóo fún àwọn orílẹ̀-èdè ní alaafia,ilẹ̀ ìjọba rẹ̀ yóo jẹ́ láti òkun dé òkunati láti odò Yufurate títí dé òpin ayé.

11 Ìwọ ní tìrẹ, nítorí ẹ̀jẹ̀ tí mo fi bá ọ dá majẹmu,n óo dá àwọn eniyan rẹ tí a kó lẹ́rú sílẹ̀ láti inú kànga tí kò lómi.

12 Ẹ pada sí ibi ààbò yín,ẹ̀yin tí a kó lẹ́rú lọ tí ẹ sì ní ìrètí;mo ṣèlérí lónìí pé,n óo dá ibukun yín pada ní ìlọ́po meji.

13 Nítorí mo ti tẹ Juda bí ọrun mi,mo sì ti fi Efuraimu ṣe ọfà rẹ̀.Ìwọ Sioni, n óo lo àwọn ọmọ rẹ bí idà,láti pa àwọn ará Giriki run,n óo sì fi tagbára tagbára lò yínbí idà àwọn jagunjagun.

14 OLUWA yóo fara han àwọn eniyan rẹ̀,yóo ta ọfà rẹ̀ bíi mànàmáná.OLUWA Ọlọrun yóo fọn fèrè ogunyóo sì rìn ninu ìjì líle ti ìhà gúsù.

15 OLUWA àwọn ọmọ ogun yóo dáàbò bo àwọn eniyan rẹ̀.Wọn óo borí àwọn ọ̀tá wọn,wọn óo fi idà pa àwọn ọ̀tá wọn,ẹ̀jẹ̀ wọn yóo sì máa ṣàn bíi ti ẹran ìrúbọ,tí a dà sórí pẹpẹ,láti inú àwo tí wọ́n fi ń gbe ẹ̀jẹ̀ ẹran.