19 Ìwọ gbàgbọ́ pé Ọlọ́run kan ní ó ń bẹ; ó dára! Àwọn ẹ̀mí èṣù pẹ̀lú gbàgbọ́ bẹ́ẹ̀, wọ́n sì wá rìrì.
20 Ṣùgbọ́n, ìwọ aláìmòye ènìyàn, ìwọ ha fẹ́ ní ìdánilójú pé, ìgbàgbọ́ ní àìsí iṣẹ́ rere asán ni?
21 Kí ha í ṣe nípa iṣẹ́ ni a dá Ábúrámù baba wa láre, nígbà tí ó fi Ísákì ọmọ rẹ̀ rúbọ lórí pẹpẹ?
22 Ìwọ rí i pé ìgbàgbọ́ rẹ bá iṣẹ́ rìn, àti pé nípa iṣẹ́ rere ni a sọ ìgbàgbọ́ di pípé.
23 Ìwé mímọ́ sì ṣẹ́ tí ó wí pé, “Ábúrámù gba Ọlọ́run gbọ́, a sì kà á sí òdodo fún un,” a sì pè é ní ọ̀rẹ́ Ọlọ́run.
24 Ǹjẹ́ ẹ̀yin rí i pé nípa iṣẹ́ rere ni à ń dá ènìyàn láre, kì í ṣe nípa ìgbàgbọ́ nìkan.
25 Gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú kí a dá Ráhábù panṣágà láre nípa iṣẹ́ bí, nígbà tí ó gba àwọn amí, tí ó sì rán wọn jáde gba ọ̀nà mìíràn?