6 Bí ó bá ń bínú ta ló lè dúró?Ta ló lè farada ibinu gbígbóná rẹ̀?Ìrúnú rẹ̀ a máa ru jáde bí ahọ́n iná,a sì máa fọ́ àwọn àpáta níwájú rẹ̀.
7 OLUWA ṣeun,òun ni ibi ààbò ní ọjọ́ ìdààmú;ó sì mọ àwọn tí wọn ń sálọ sọ́dọ̀ rẹ̀ fún ààbò.
8 Bí odò tí ó kún bo bèbè rẹ̀ni yóo ṣe mú ìparun bá àwọn ọ̀tá rẹ̀;yóo sì lépa àwọn ọ̀tá rẹ̀ bọ́ sí inú òkùnkùn.
9 Èrò ibi wo ni ẹ̀ ń gbà sí OLUWA?Yóo wulẹ̀ pa yín run patapata ni;kò sì sí ẹni tí OLUWA yóo gbẹ̀san lára rẹ̀ lẹ́ẹ̀kantí yóo lè ṣẹ̀ ẹ́ lẹẹkeji.
10 Wọn yóo jóná bí igbó ẹlẹ́gùn-ún tí ó dí,àní bíi koríko gbígbẹ.
11 Ṣebí ọ̀kan ninu yín ni ó ń gbìmọ̀ burúkú sí OLUWA, tí ó sì ń fúnni ní ìmọ̀ràn burúkú?
12 OLUWA wí pé: “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ará Siria lágbára, tí wọ́n sì pọ̀, a óo pa wọ́n run, wọn yóo sì parẹ́. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti jẹ ẹ̀yin ọmọ Juda níyà tẹ́lẹ̀, n kò ní jẹ yín níyà mọ́.