15 Ọmọ yìí yóo mú kí adùn ayé rẹ sọjí, yóo sì jẹ́ olùtọ́jú fún ọ ní ọjọ́ ogbó rẹ, nítorí iyawo ọmọ rẹ tí ó fẹ́ràn rẹ, tí ó sì ju ọmọkunrin meje lọ ni ó bímọ fún ọ.”
16 Naomi bá gba ọmọ náà, ó tẹ́ ẹ sí àyà rẹ̀, ó sì di olùtọ́jú rẹ̀.
17 Àwọn obinrin àdúgbò bá sọ ọmọ náà ní Obedi, wọ́n ń sọ káàkiri pé, “A bí ọmọkunrin kan fún Naomi.” Obedi yìí ni baba Jese tíí ṣe baba Dafidi.
18 Àwọn atọmọdọmọ Peresi nìwọ̀nyí: Peresi ni baba Hesironi;
19 Hesironi bí Ramu, Ramu bí Aminadabu;
20 Aminadabu bí Naṣoni; Naṣoni bí Salimoni;
21 Salimoni bí Boasi, Boasi bí Obedi;