26 Àwọn ohun ọ̀sìn wa gbọdọ̀ lọ pẹ̀lú wa, a kì yóò fi pátákò ẹṣẹ̀ ẹran sílẹ̀. A ní láti lò lára wọn fún sínsìn Olúwa Ọlọ́run wa, ìgbà tí a bá sì dé ibẹ̀ ni a ó to mọ̀ ohun ti a ó lò láti fi sìn Olúwa.”
27 Ṣùgbọ́n Olúwa ṣé ọkàn Fáráò le, kò sì ṣetan láti jẹ́ kí wọn lọ.
28 Fáráò sọ fún Mósè pé, “Kúrò ní iwájú mi! Rí i dájú pé o kò wá sí iwájú mi mọ́! Ọjọ́ tí ìwọ bá rí ojú mi ni ìwọ yóò kú.”
29 Mósè sì dáhùn pé, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wí, “Èmi kí yóò wá sí iwájú rẹ mọ́.”