5 Ibú omi bò wọ́n mọ́lẹ̀;Wọ́n sì rì sí ìsàlẹ̀ omi òkun bí òkúta.
6 “Ọwọ́ ọ̀tún rẹ, Olúwa,pọ̀ ní agbára.Ọwọ́ ọ̀tún rẹ, Olúwa,fọ́ àwọn ọ̀ta túútúú.
7 Nínú agbára ńlá rẹ ti ó tóbiìwọ bi àwọn ti ó dìde sí ọ ṣubú.Ìwọ rán ìbínú gbígbóná rẹ;Tí ó run wọ́n bí ìgémọ́lẹ̀ ìdí koríko
8 Pẹ̀lú èémí imú rẹ ni omi fi ńwọ́jọ pọ̀Ìsàn omi dìde dúró bí odi;Ibú omi sì dìpọ̀ láàrin òkun.
9 “Ọ̀ta ń gbéraga, ó ń wí pé:‘Èmi ó lépa wọn, èmi ó bá wọn.Èmi ó pín ìkógun;Èmi ó tẹ́ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ mi lọ́run lára wọn.Èmi yóò fa idà mi yọ, ọwọ́ mi yóò pa wọ́n run.’
10 Ìwọ fẹ́ èèmí rẹòkun ru bò wọ́n mọ́lẹ̀wọ́n rì bí òjéni àárin omi ńlá.
11 “Ta ni nínú àwọn òrìṣà tó dàbí rẹ, Olúwa?Ta ló dàbí rẹ:ní títóbi,ní mímọ́ Ẹlẹ́rù ni yìnTí ń se ohun ìyanu?