Ékísódù 28:38-43 BMY

38 Kí ó wà níwájú orí Árónì, kí ó sì lè máa ru ẹ̀bi tí ó jẹ mọ́ ẹ̀bùn mímọ́ ti àwọn ọmọ Ísírẹ́lì ti yà sí mímọ́, èyíkéyìí tí ẹ̀bùn wọn lè jẹ́. Yóò máa wà níwájú orí Árónì nígbà gbogbo, kí wọn lè jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún Olúwa.

39 “Ìwọ yóò sì fi ọ̀gbọ̀ dáradára hun ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀, ìwọ yóò sì fi ọ̀gbọ̀ dáradára ṣe fìlà. Iwọ yóò sì fi ṣẹ́ abẹ́rẹ́ ṣe ọ̀já àmùrè.

40 Ìwọ yóò sì dá ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀, ọ̀já àmùrè àti ìgbàrí fún àwọn ọmọ Árónì, láti fún wọn ní ọ̀ṣọ́ àti ọlá.

41 Lẹ́yìn tí ìwọ ti fi àwọn aṣọ wọ̀nyí wọ Árónì arákùnrin rẹ, ìwọ yóò sì fi wọ àwọn ọmọ rẹ̀ pẹlú, ìwọ óta òróró sí wọn ní orí, ìwọ yóò sì ya wọ́n sí mímọ́. Ìwọ yóò sì Sọ wọ́n di mímọ́, kí wọn kí o lè máa se iṣe àlùfáà.

42 “Ìwọ yóò dá aṣọ àwòtẹ́lẹ̀ fún wọn, kí wọn lè máa fi bo ara wọn, kí ó dé ìbàdí dé itan.

43 Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ gbọdọ̀ wọ̀ wọ́n nígbàkugbà tí wọ́n bá wọ àgọ́ àjọ lọ tàbí nígbà tí wọ́n bá súnmọ́ pẹpẹ láti ṣiṣẹ́ ní ibi mímọ́ kí wọn kí ó má ba à dẹ́sẹ̀, wọn a sì kú.“Èyí jẹ́ ìlànà láéláé fún Árónì àti fún irú ọmọ rẹ̀ lẹ́yìn rẹ̀.