7 Nígbà náà ni ìwọ yóò sì mú òrórò ìtasórí, ìwọ yóò sì yà á sí mímọ́ nípa dída òróró sí i ní orí.
8 Ìwọ yóò sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ ìwọ yóò sì fi aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀ wọ́n
9 ìwọ yóò sì fi fìlà dé wọn ni orí. Nígbà náà fi ọ̀já àmùrè di Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀. Iṣẹ́ àlùfáà yóò máa jẹ́ ti wọn ní ìlànà títí ayé. Báyìí ni ìwọ yóò sì ya Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ sí mímọ́.
10 “Ìwọ yóò sì mú akọ màlúù wá ṣíwájú àgọ́ àjọ, Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò sì fi ọwọ́ lé wọn ní orí.
11 Ìwọ yóò sì pa àwọn akọ màlúù náà níwájú Olúwa ní ẹnu ọ̀nà àgọ́ àjọ.
12 Ìwọ yóò sì mú nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù náà, ìwọ yóò sì fi ìka rẹ tọ́ ọ sára ìwo pẹpẹ náà, kí o sì da gbogbo ẹ̀jẹ̀ tó kù sí ìṣàlẹ̀ pẹpẹ náà.
13 Kí o mú gbogbo ọ̀rá tí ó yí inú ká, èyí tí ó bo ẹ̀dọ̀ àti ìwé méjèèjì pẹ̀lú ọ̀rá tí ó wà lára wọn, ìwọ yóò sì sun wọ́n lórí pẹpẹ.