20 Ṣùgbọ́n,” ó wí pé, “Ìwọ kò le è rí ojú mi, nítorí kò sí ẹnìkan tó rí mi, tí ó lè yè.”
21 Olúwa sì wí pé, “Ibì kan wà lẹ́gbẹ̀ ẹ́ ọ̀dọ̀ mi, níbi tí o ti lè dúró lórí àpáta.
22 Nígbà tí ògo mi bá kọjá, èmi yóò gbé ọ sínú pàlàpálá àpáta, èmi yóò sì bò ọ́ pẹ̀lú ọwọ́ mi títí èmi yóò fi rékọjá.
23 Nígbà tí èmi yóò mú ọwọ́ mi kúrò, ìwọ yóò sì rí ẹ̀yìn mi; ṣùgbọ́n ojú mi ni o kò ní rí.”