Ẹ́sítà 7:1-7 BMY

1 Ọba àti Hámánì sì lọ sí àpèjẹ pẹ̀lú Ẹ́sítà ayaba,

2 Bí wọ́n sì ṣe ń mu wáìnì ní ọjọ́ kejì yìí, ọba sì tún béèrè pé, “Ẹ́sítà ayaba, kí ni ẹ̀bẹ̀ rẹ? A ó sì fi fún ọ. Kí ni ìbéèrè rẹ? Bí ó ti lẹ̀ jẹ́ ìdajì ìjọbaà mi, n ó fi fún ọ.”

3 Nígbà náà ni ayaba Ẹ́sítà dáhùn, “Bí èmi bá rí ojú reree rẹ, ìwọ ọba, bí ó bá sì tẹ́ ọláà ńlá à rẹ lọ́rùn, fún mi ní ẹ̀míì mi-èyí ni ẹ̀bẹ̀ mi. Kí o sì pa àwọn ènìyàn mi mọ́-èyí ni ìbéèrè mi.

4 Nítorí a ti ta èmi àti àwọn ènìyàn mi fún àwọn tí yóò pa wá run, à ti ṣe ìdájọ́ wa fún pípa àti píparẹ́. Bí a bá ti lẹ̀ tàwá bí ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ǹbá dákẹ́, nítorí irú ìpọ́njú bẹ́ẹ̀ kò tó èyí tí à ń yọ ọba lẹ́nu sí.”

5 Ọba Ṣéríṣésì sì bi Ésítà ayaba léèrè pé, “ta a ni ẹni náà? Níbo ni ẹni náà wà tí kò bẹ̀rù láti ṣe irú nǹkan bẹ́ẹ̀?”

6 Ésítà sọ wí pé, “alátakò àti ọ̀ta náà ni Hámánì aláìníláárí yìí,”Nígbà náà ni Hámánì wárìrì níwájú ọba àti ayaba.

7 Ọba sì dìde pẹ̀lú ìbínú, ó fi wáìnì sílẹ̀ ó sì jáde lọ sí àgbàlá ààfin. Ṣùgbọ́n nígbà tí Hámánì, ti ríi dájú pé ọba ti pinnu láti pa òun, ó dúró lẹ́yìn láti bẹ Ẹ́sítà ayaba nítorí ẹ̀míi rẹ̀.