2 Wọ́n rúbọ sí Báálì bí mo ṣe ń pe Ísírẹ́lì síbẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń sá kúrò lọ́dọ̀mi jìnnà sí i: wọn rúbọ sí báálímu,wọn sì fi tùràrí jóná sí ère fínfín.
3 Lóòtọ́ mo kọ́ Éfúráímù pẹ̀lú ní ìrìnmo di wọ́n mú ní apá,ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀pé mo ti mú wọn lára dá.
4 Mo fó okùn ènìyàn fà wọ́nàti ìdè ìfẹ́.Mo mú àjàgà kúrò ni ọrùn wọnMo sì farabalẹ̀ fún wọn ni oúnjẹ.
5 “Ṣé wọn ò wá ní padà sí Éjíbítì bíṢé Ásíríà kò sì ní jẹ ọba lé wọn lórí bínítorí pé wọ́n kọ̀ jálẹ̀ láti ronú pìwàdà?
6 Idà yóò kọ mọ̀nà ní gbogbo ìlú wọnyóò si bá gbogbo irin ẹnú odi ìlú wọn jẹ́yóò sì fòpin sí gbogbo èrò wọn.
7 Àwọn ènìyàn mi ti pinnu láti pẹ̀yìndà kúrò lọ́dọ̀ miBí wọ́n tilẹ̀ pè wọ́n sọ́dọ̀ ọ̀gá-ògo júlọ,kò ní gbé wọn ga rárá.
8 “Báwo ni èmi ó ṣe fi ọ́ sílẹ̀, Éfúráímù?Báwo ni èmi ó ṣe yọ̀ǹda rẹ̀, Ísírẹ́lìBáwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Ádímà?Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Ṣébóímù?Ọkàn mi yípadà nínú miÀánú mi sì ru sókè