4 “Èmi wo àgàbàgebè wọn sàn,Èmi ó sì fẹ́ràn wọn, lọ́fẹ̀ẹ́,nítorí ìbínú mi ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ ọ wọn.
5 Èmi o dàbí ìrì sí Ísírẹ́lìwọn o sì yọ ìtànná bi ewéko lílìyóò sì ta gbòngbòkédárì ti Lébánónì
6 Àsẹ̀sẹ̀yọ ẹ̀ka rẹ̀ yóò dàgbà,Didan ẹwà yóò rẹ̀ dànù bí igi ólífìÒórùn rẹ yóò sì dàbí igi sídà ti Lébánónì.
7 Àwọn ènìyàn yóò tún padà gbé lábẹ́ òjijì rẹ̀.Yóò rúwé bi ọkà.Yóò sì yọ ìtànná bi àjàrà,òórùn rẹ yóò dàbí ti wáìnì Lébánónì.
8 Ìwọ Éfúráímù; Kín ló tún kù tí mo ní ṣe pẹ̀lú ère òrìṣà?Èmi ó daba! lóhùn, èmi o sì ṣe ìtọ́jú rẹ.Mo dàbí igi tó ń fi gbogbo ìgbà tutù,èso tí ìwọ ń so si ń wá láti ọ̀dọ̀ mi.”
9 Ta ni ọlọgbọ́n? Òun yóò mòye àwọn nǹkan wọ̀nyíTa a ní ó mọ̀? Òun yóò ní ìmọ̀ wọn.Tí tọ́ ni ọ̀nà Olúwaàwọn olódodo si ń rìn nínú wọnṢùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ nìyóò kọsẹ̀ nínú wọn.