30 Kí àlùfáà fi ọ̀kan rúbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti èkejì fún ẹbọ sísun. Báyìí ni yóò ṣe ètùtù fún un, níwájú Olúwa fún àìmọ́ ìsun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀.
31 “ ‘Ẹ ya ará Ísírẹ́lì sọ́tọ̀ kúrò nínú ohun tí ó ń sọ wọ́n di aláìmọ́ kí wọ́n má báa kú nínú àìmọ́ wọn nípa bíba ibùgbé mímọ́ mi jẹ́: Èyí tí ó wà láàrin wọn.’ ”
32 Ìwọ̀nyí ni àwọn òfin fún ọkùnrin tí ó ni ìṣunjáde fún ẹnikẹ́ni tí a sọ di àìmọ́ nípa ìṣunjáde nǹkan ọkùnrin rẹ̀.
33 Fún obìnrin ní nǹkan oṣù rẹ̀, fún ọkùnrin tàbi obìnrin tí ó ní ìṣunjáde, àti fún ọkùnrin tí ó ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin tí ó jẹ́ aláìmọ́.