30 Nítorí àwa mọ ẹni tí o wí pé: Ẹ̀san niti èmi, Olúwa wí pé, “Èmi o gbẹ̀san.” Àti pẹ̀lú, “Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.”
31 Ohun ẹ̀rù ni láti ṣubú sí ọwọ́ Ọlọ́run alààyè.
32 Ṣùgbọ́n ẹ rántí ọjọ́ ìṣáájú nínú èyí tí, nígbà tí a ti ṣi yin lójú, ẹ fi ara da wàhálà ńlá ti ìjìyà;
33 Lápakan, nígbà tí a ṣọ yín di ìran wíwò nípa ẹ̀gàn àti ìpọ́njú; àti lápakan, nígbà tí ẹ̀yin di ẹ̀gbẹ àwọn tí a ṣe bẹ́ẹ si.
34 Nítorí ẹ̀yin bá àwọn tí ó wà nínú ìdè kẹ́dùn, ẹ sì fi ayọ̀ gba ìkólọ ẹrù yin, nítorí ẹ̀yin mọ nínú ara yin pé, ẹ ni ọrọ̀ tí ó wà títí, tí ó sì dára jù bẹ́ẹ̀ lọ.
35 Nítorí náà ẹ má ṣe gbé ìgboyà yín sọnù, èyí ti o ni èrè ńlá.
36 Nítorí ẹ̀yin kò le ṣe aláìní suuru, nítorí ìgbà tí ẹ̀yin bá ti ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run tan kí ẹ̀yin le gba ìlérí náà.