Amosi 9:9-15 BM

9 “N óo pàṣẹ pé kí wọ́n gbo gbogbo Israẹli jìgìjìgì láàrin gbogbo orílẹ̀-èdè, bí ìgbà tí wọ́n bá fi ajọ̀ ku èlùbọ́, ṣugbọn kóró kan kò ní bọ́ sílẹ̀.

10 Gbogbo àwọn tí wọn ń dẹ́ṣẹ̀ láàrin àwọn eniyan mi ni ogun yóo pa, gbogbo àwọn tí wọ́n ń sọ pé, ‘Ibi kankan kò ní bá wa!’

11 “Ní ọjọ́ náà, n óo gbé àgọ́ Dafidi tí ó ti wó ró. N óo tún odi rẹ̀ mọ, n óo tún un kọ́ yóo sì rí bí ó ti wà tẹ́lẹ̀ rí.

12 Àwọn ọmọ Israẹli yóo ṣẹgun àwọn tí wọ́n kù ní Edomu, ati gbogbo orílẹ̀-èdè tí à ń fi orúkọ mi pè. Èmi OLUWA, tí n óo ṣe bí mo ti wí, èmi ni mo sọ bẹ́ẹ̀.

13 “Ọjọ́ ń bọ̀, tí ọkà yóo so jìnwìnnì,tóbẹ́ẹ̀ tí wọn kò ní lè kórè rẹ̀ tánkí àkókò gbígbin ọkà mìíràn tó dé.Ọgbà àjàrà yóo so,tóbẹ́ẹ̀ tí a kò ní lè fi ṣe waini tánkí àkókò ati gbin òmíràn tó dé.Ọtí waini dídùn yóo máa kán sílẹ̀ lórí àwọn òkè ńlá,ọtí waini yóo sì máa ṣàn jáde lára àwọn òkè kéékèèké.

14 N óo dá ire Israẹli, àwọn eniyan mi, pada,wọn yóo tún àwọn ìlú tí wọ́n ti wó kọ́,wọn yóo sì máa gbé inú wọn.Wọn yóo gbin àjàrà,wọn yóo sì mu ọtí waini rẹ̀.Wọn yóo ṣe ọgbà,wọn yóo sì jẹ èso rẹ̀.

15 N óo fẹsẹ̀ àwọn eniyan mi múlẹ̀lórí ilẹ̀ tí mo fún wọn,a kò sì ní ṣí wọn nípò pada mọ́lórí ilẹ̀ tí mo fún wọn.Èmi OLUWA Ọlọrun yín ni mo sọ bẹ́ẹ̀.”