Ẹkún Jeremaya 2:1-7 BM

1 Ẹ wò bí OLUWA ti fi ibinufi ìkùukùu bo Sioni mọ́lẹ̀.Ó ti wọ́ ògo Israẹli luláti òkè ọ̀run sórí ilẹ̀ ayé;kò tilẹ̀ ranti àpótí ìtìsẹ̀ rẹ̀ ní ọjọ́ ibinu rẹ̀.

2 OLUWA ti pa gbogbo ibùgbé Jakọbu run láìsí àánú.Ó ti fi ibinu wó ibi ààbò Juda lulẹ̀.Ó ti rẹ ìjọba ati àwọn aláṣẹ rẹ̀ sílẹ̀,ó fi àbùkù kàn wọ́n.

3 Ó ti fi ibinu gbígbóná rẹ̀,pa àwọn alágbára Israẹli;ó kọ̀, kò ràn wọ́n lọ́wọ́,nígbà tí àwọn ọ̀tá dojú kọ wọ́n.Ó jó àwọn ọmọ Jakọbu bí iná,ó sì pa gbogbo ohun tí wọn ní run.

4 Ó kẹ́ ọfà rẹ̀ bí ọ̀tá,ó múra bí aninilára.Gbogbo ògo wa ló parun lójú wa,ó sì tú ibinu rẹ̀ jáde bí iná, ninu àgọ́ Sioni.

5 OLUWA ṣe bí ọ̀tá,ó ti pa Israẹli run.Ó ti pa gbogbo ààfin rẹ̀ run,ó sọ àwọn ibi ààbò rẹ̀ di àlàpàó sì sọ ọ̀fọ̀ ati ẹkún Juda di pupọ.

6 Ó wó àgọ́ rẹ̀ lulẹ̀,bí ìgbà tí eniyan wó ahéré oko.Ó pa gbogbo ibi tí wọ́n ti ń ṣe àwọn àjọ̀dún tí a yà sọ́tọ̀ run.OLUWA ti fi òpin sí àwọn àjọ̀dún tí a yà sọ́tọ̀, ati ọjọ́ ìsinmi ní Sioni.Ó sì ti fi ibinu gbígbóná rẹ̀,kọ ọba ati alufaa sílẹ̀.

7 OLUWA kò bìkítà fún pẹpẹ rẹ̀ mọ́,ó sì ti kọ ibi mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀.Ó ti fi odi ààfin rẹ̀ lé àwọn ọ̀tá lọ́wọ́;wọ́n pariwo ńlá ninu ilé OLUWAgẹ́gẹ́ bíi ti ọjọ́ àjọ̀dún tí a yà sọ́tọ̀.